Bí ènìyàn se lè jẹ́ ọmọ Orílẹ̀ èdè Nàìjíríà

25(1) O lè jẹ́ ọmọ bíbí orílẹ̀ èdè Nàìjíríà nípasẹ̀ ibi tí:

  1. a) wọ́n bá bí ẹ ní Nàìjíríà síwájú ọjọ́ kiní oṣù kẹ̀wá ọdún 1960 tàbí tí bàbá, ìyá, tàbí ìyá bàbá, ìyá màmá, bàbá bàbá tàbí bàbá ìyá rẹ jẹ́ ọmọ ìlú kan ní Nàìjíríà. Ṣùgbọ́n, o kì yóò jẹ́ ọmọ orílẹ̀ èdè yí tí wọ́n kò bá bí àwọn òbí rẹ tàbí àwọn òbí-òbí rẹ ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà.
  2. b) wọ́n bá bí ẹ ní orílẹ̀ èdè míìràn lẹ́yìn ọjọ́ kiní, ọ̀sẹ̀ kẹwà ọdún 1960, àti wí pé ìyá rẹ tàbí bàbá rẹ, tàbí àwọn òbí bàbá tàbí ìyá rẹ jẹ́ ọmọ Nàìjíríà.
  3. c) A bí ẹ ní orílẹ̀ èdè míìràn ṣùgbọ́n, bàbá tàbí ìyá rẹ jẹ́ ọmọ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà.

26(1) O lè jẹ́ ọmọ Nàìjíríà nípasẹ̀ fífi orúkọ sílẹ̀ ṣùgbọ́n, kí o tó lè ṣe èyí, o gbọ́dọ̀ jẹ́ ìwọ̀nyí:

  1. a) oníwà rere;
  2. b) o gbọ́dọ̀ fi ìwà hàn pé o fẹ́ maa gbé ní orílẹ̀ èdè Nàìjíríà;
  3. c) O gbọ́dọ̀ ṣe Ìbúra láti bọ̀wọ̀ fún òfin Nàìjíríà àti láti dá àbò bó.

(2) Apá òfin yìí bá ẹ wí tí o bá jẹ́:

  1. a) obìnrin tí ó fẹ́ ọmọ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà
  2. b) a bí ọ ní orílẹ̀ èdè míìràn ṣùgbọ́n àwọn òbí- bàbá tàbí ìyá rẹ jẹ́ ọmọ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà.

27 (1) O lè jé ọmọ orílẹ̀ èdè yíì nípasẹ̀ ìdarapọ̀ tó bá kún ojú òṣùwọ̀n; o lè bèrè fún ìwé ẹ̀rí ìdarapọ̀ láti jẹ ọmọ orílẹ̀ èdè yíì lọ́dọ̀ Ààrẹ Nàìjíríà.

(2) o lè bèrè fún ìdarapọ̀ láti jẹ́ ọmọ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà àyàfi tí o bá tẹ́ Ààrẹ lọ́rùn wí pé:

  1. a) o ti pé ọmọ ọdún méjìdínlógún àti sókè;
  2. b) o jẹ́ oníwà rere;
  3. c) O ti fihàn wí pé o fẹ́ maa gbé ní Nàìjíríà;
  4. d) Nípasẹ̀ Ìwádìí Gómínà Ìpínlẹ̀ tí o ń gbé, o fihàn wí pé agbègbè tí o ń gbé gbà ọ́, o sì ti mo ìgbé ayé àwọn ènìyàn níbi tí o ń gbé, àti wí pé, o fẹ́ maa gbé ìlú náà.
  5. e) ó tó láti mú tàbí ó ti ń mú ìtẹsíwájú bá ìrànwọ́ ìtẹsíwájú Nàìjíríà;
  6. f) ó tí ṣe ìbúra láti bọ̀wọ̀ fún ìwé òfin Nàìjíríà àti láti dábò bò.
  1. g) kí ó tó bèrè, ó ti gbé ní Nàìjíríà fún ọdún márùndínlógún, tàbí ó ti gbé láì kúrò ní Nàìjíríà fún oṣù méjìlá àti láàrin ogún ọdún kó tó bèrè fún ìdarapọ̀ náà, tí ó sì ti gbé ní orílẹ̀ èdè yíì fún ọdún márùndínlógún lápapọ̀.

28(1) O kì yóò jẹ́ ọmọ Nàìjíríà mọ́ tí o kò bá jẹ́ ọmọ bíbí orílẹ̀ èdè yíì tí o tún gba ìjẹ́ ọmọ ìlú orílẹ̀ èdè míìràn nípasẹ̀ ìforúkọ sílẹ̀ tàbí ìdarapọ̀.

(2) tí o bá kìíṣe ọmọ bíbí orílẹ̀ èdè míìràn tí o sì fẹ́ jẹ́ ọmọ Nàìjíríà nípa ìforukọsílẹ̀ tàbí ìdarapọ̀, ìjẹ́ ọmọ Nàìjíríà rẹ ní yóò ní ìdánwò àti gbèdeke títí da àsìkò tí o kéde wí pé o kìíṣe ọmọ orílẹ̀ èdè míìràn mọ́. Èyí ni o gbọ́dọ̀ ṣe láàrín oṣù méjìlá ní ìgbà tí o di ọmọ Nàìjíríà nípasẹ̀ ìforukọsílẹ̀ tàbí ìdarapọ̀.

29(1) Àgbàlagbà tó bá tó ọmọ ọdún méjìdínlógún tí kò fẹ́ jẹ́ ọmọ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà mọ́ lè kéde èróńgbà rẹ̀ ní ọ̀nà wọ̀nyí.

(2) Ààrẹ Nàìjíríà yóò jẹ́kí ìkéde náà wà ní àkọsílẹ̀. Tí ó bá ti wà ní àkọsílẹ̀, ẹni tó ṣe ìkéde náà kòní jẹ́ ọmọ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà mọ́.

(3) Ààrẹ Nàìjíríà lè má jẹ́kí ìkéde náà wà ní àkọsílẹ tí:

  1. a) Tí ìkéde náà bá wáyé ní ìgbà tí ogun ńjà ní Nàìjíríà tàbí
  2. b) Tí Ààrẹ bári wí pé àkosílẹ̀ náà kì ìṣe fún àǹfàní Nàìjíríà.

(4) Kí ènìyàn tó lè jẹ́ àgbàlagbà bí a se kọ́ ní apá kọkàndínlọ́gbọ̀n àti óókan kékeré 29(1) apá òfin yìí, ẹni náà ti tó ọmọ ọdún méjìdínlógún sókè

  1. b) Ìyawó ilé àgbàlagbà jẹ́ eni tó tí tó ọdún méjìdínlógún sókè.

30 (1) Ààrẹ lè dá ẹni tó ti gba ìdarapọ̀ láti jẹ́ ọmọ Nàìjíríà dúró tí Ààrẹ bá ri wí pé láàrín ọdún méje tó ti darapọ̀ láti jẹ́ ọmọ orílẹ̀ èdè yíì, ó ti gba ìdajọ́ ẹ̀wọ̀n ọlọ́dún mẹ́ta sókè.

(2) Ààrẹ lè dá ẹni tó gba ìwé jíjẹ́ ọmọ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà dúró tí Ààrẹ bá ri wí pé nínu ìkọsílẹ̀ ilé ẹjọ́ gíga tàbí nínu ìwádìí, ẹni náà wu ìwà tàbí sọ̀rọ̀ tí kìíṣe olóotó sí Nàìjíríà tàbí ní ìgbà tí Nàìjíríà ńja ogun, ẹni náà ní àṣepọ̀ pẹ̀lú àwọn ọ̀tá lòdì sí Nàìjíríà. Irú ẹni bẹ́è kò gbọdọ̀ jẹ́ ọmọ bíbí Nàìjíríà.

31 (1) Ní apá òfin yíì, òbí tàbí àwon òbí-òbí ènìyàn yóò jẹ́ ọmọ Nàìjíríà tóbá jẹ́ wí pé ní ìgbà tí wọ́n bí wọn, wọ́n kún ojú òṣùwọ̀n láti jẹ́ ọmọ bíbí Nàìjíríà tó bá jẹ́ wí pé wọ́n wà láyé ní Ọjọ́ kiní, Oṣù kẹwà ọdún 1960.

32 (1) Ààrẹ lè ṣe ìlànà ní ìbámu pẹ̀lú apá òfin yìí láti mú ohun tó wà nínu ìwe òfin yìí ṣe àti láti fún àwọn aya àti ọkọ ọmọ orílẹ̀ èdè Nàìjíríà láti orílẹ̀ èdè míìràn gbé ní Nàìjíríà bí wọ́n kò bá fẹ́ jẹ́ ọmọ orílẹ̀ èdè yíì.

(2) Gbogbo ìlànà tí Ààrẹ bá ṣe ní ìbámu pẹ̀lú àwọn ọ̀rọ̀ apá òfin yìí ní ó gbọ́dọ̀ fi ṣọwọ́ sí Ilé Ìgbìmọ̀ Aṣòfin Àpapọ̀.